A. Oni 19:21-27 YCE

21 Bẹ̃li o mú u wá sinu ile rẹ̀, o si fi onjẹ fun awọn kẹtẹkẹtẹ: nwọn wẹ̀ ẹsẹ̀ wọn, nwọn jẹ nwọn si mu.

22 Njẹ bi nwọn ti nṣe ariya, kiyesi i, awọn ọkunrin ilu na, awọn ọmọ Beliali kan, yi ile na ká, nwọn si nlù ilẹkun; nwọn si sọ fun bale ile na ọkunrin arugbo nì, pe, Mú ọkunrin ti o wọ̀ sinu ile rẹ nì wá, ki awa ki o le mọ̀ ọ.

23 Ọkunrin, bale ile na si jade tọ̀ wọn lọ, o si wi fun wọn pe, Bẹ̃kọ, ẹnyin arakunrin mi, emi bẹ̀ nyin, ẹ má ṣe hùwa buburu; nitoriti ọkunrin yi ti wọ̀ ile mi, ẹ má ṣe hùwa wère yi.

24 Kiyesi i, ọmọbinrin mi li eyi, wundia, ati àle rẹ̀; awọn li emi o mú jade wá nisisiyi, ki ẹnyin tẹ́ wọn li ogo, ki ẹnyin ṣe si wọn bi o ti tọ́ li oju nyin: ṣugbọn ọkunrin yi ni ki ẹnyin má ṣe hùwa wère yi si.

25 Ṣugbọn awọn ọkunrin na kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀: ọkunrin na si mú àle rẹ̀, o si mú u tọ̀ wọn wá; nwọn si mọ̀ ọ, nwọn si hù u niwakiwa ni gbogbo oru na, titi o fi di owurọ̀: nigbati o si di afẹmọjumọ́ nwọn jọwọ rẹ̀ lọwọ lọ.

26 Nigbana li obinrin na wá li àfẹmọjumọ́, o si ṣubu lulẹ, li ẹnu-ilẹkun ile ọkunrin na nibiti oluwa rẹ̀ gbé wà, titi ilẹ fi mọ́.

27 Oluwa rẹ̀ si dide li owurọ̀, o si ṣi ilẹkun ile na, o si jade lati ba ọ̀na rẹ̀ lọ: si kiyesi i obinrin na, àle rẹ̀, ṣubu lulẹ li ẹnu-ilẹkun ile na, ọwọ́ rẹ̀ si wà li ẹnu-ọ̀na na.