8 Ilẹ na kì yio ha warìri nitori eyi, ati olukuluku ẹniti o ngbe inu rẹ̀ kì yio ha ṣọ̀fọ? yio si rú soke patapata bi kikún omi; a o si tì i jade, a o si tẹ̀ ẹ rì, gẹgẹ bi odò Egipti.
9 Yio si ṣe li ọjọ na, li Oluwa Ọlọrun wi; emi o si mu ki õrùn ki o wọ̀ lọsan, emi o si mu aiye ṣu òkunkun li ọ̀san gangan:
10 Emi o si yi àse nyin padà si ọ̀fọ, ati orin nyin gbogbo si ohùn-rére ẹkún: emi o si mu aṣọ ọ̀fọ wá si ẹgbẹ̀ gbogbo, ati pipá ori, si gbogbo ori; emi o si ṣe e ki o dàbi iṣọ̀fọ fun ọmọ kanṣoṣo ti a bi; ati opin rẹ̀ bi ọjọ kikorò.
11 Kiyesi i, ọjọ na de, li Oluwa Ọlọrun wi, emi o rán iyàn wá si ilẹ na, kì iṣe iyàn onjẹ, tabi ongbẹ fun omi, ṣugbọn iyàn gbigbọ́ ọ̀rọ Oluwa:
12 Nwọn o si ma rìn kiri lati okun de okun, ati lati ariwa ani titi de ila-õrun, nwọn o sare siwá sẹhìn lati wá ọ̀rọ Oluwa, nwọn kì yio si ri i.
13 Li ọjọ na li awọn arẹwà wundia, ati awọn ọdọmọkunrin yio daku fun ongbẹ.
14 Awọn ti o fi ẹ̀ṣẹ Samaria bura, ti nwọn si wipe, Iwọ Dani, ọlọrun rẹ mbẹ lãyè! ati ọ̀na Beerṣeba mbẹ lãyè! ani nwọn o ṣubu, nwọn kì yio si tún dide mọ.