45 Ṣùgbọ́n àlejò àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.
46 “Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.
47 Gbogbo àjọ Ísírẹ́lì ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.
48 “Àjòjì ti ó bá ń gbé ní àárin yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ìlà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ìlà, wọ́n kò ni jẹ ni ara rẹ̀.
49 Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárin yín.”
50 Gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè àti Árónì.
51 Àti pé ní ọjọ́ náà gan-an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.