4 aṣọ aláwọ̀ aró, aṣọ aláwọ̀ aró-fẹ́ẹ́rẹ́, aṣọ aláwọ̀ òdòdó, aṣọ funfun-láú, ìrun ewúrẹ́.
5 Awọ àgbò tí a rẹ ní pupa àti awọ ewúrẹ́-dò; igi kásíà;
6 Òróró olífì fún iná títàn, òróró olóórùn dídùn fún ìtasórí àti fún tùràrí olóórùn dídùn,
7 àti òkúta oníkì àti òkúta olówó iyebíye ti a fi ṣe ọ̀ṣọ́ sí ara ẹ̀wù éfódi àti ẹ̀wù ìgbàyà.
8 “Nígbà náà ni ìwọ yóò jẹ́ kí wọn kọ́ ibi mímọ́ fún mi. Èmi yóò sì máa gbé ní àárin wọn.
9 Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí ti mo fi hàn ọ́, nípa àpẹẹrẹ àgọ́, àti àpẹẹrẹ gbogbo ohun èlò inú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin kí ó sì ṣe é.
10 “Kí wọn kí ó fi igi kasíà ṣe àpótí, kí gígùn rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjì àti ààbọ̀, kí fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀.