Hágáì 1 BMY

Ìpè Láti Tún Ilé Olúwa Kọ́.

1 Ní ọdún kejì ọba Dáríúsì ní ọjọ́ kìn-ín ní okìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hágáì sí Serubábéli ọmọ Séítélì, Baálẹ̀ Júdà, àti Sọ́dọ̀ Jósúà ọmọ Jósédékì, olórí àlùfáà.

2 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò ti to àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’ ”

3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hágáì wí pé:

4 “Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fún ra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀sọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”

5 Ní sinsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsí ọ̀nà yín.

6 Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀; Ẹ̀yin jẹun, Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; Ẹ̀yin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”

7 Báyìí ni Olúwa alágbára wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.

8 Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà leè dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí.

9 “Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsíi,, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dáhoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀.

10 Nítorí yín ni awọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde.

11 Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí awọn òkè-ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”

12 Nígbà náà ni Sérúbábélì ọmọ Séítíélì, Jósúà ọmọ Jósédékì, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hágáì, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.

13 Nígbà náà ni Hágáì ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí.

14 Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Sérúbábẹ́lì ọmọ Séítélì sókè, olórí Júdà àti ẹ̀mí Jóṣúà ọmọ Jósédékì, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn,

15 ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dáríúsì.

orí

1 2