1 Éfúráímù ń jẹ afẹ́fẹ́;Ó n lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀ oòrùn ní gbogbo ọjọ́.Ó sì ń gbèrú nínú irọ́Ó dá májẹ̀mú pẹ̀lú ÁsíríàÓ si fi òróró ólífì ránsẹ́ sí Éjíbítì.
2 Olúwa ní ẹ̀sùn tí yóò fí kan Júdàyóò fìyà jẹ Jákọ́bù gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀yóò sì sán fún-un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
3 Láti inú oyun ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀,àti nípa ìpá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
4 Ó bá ángẹ́lì ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀Ó sunkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojú rere rẹ̀Ó bá Olúwa ní Bẹ́tẹ́lìÓ sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
5 àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀
6 Ṣùgbọ́n ìwọ́ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀;Di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo múkí ẹ sì dúró de Olúwa yín nígbà gbogbo.
7 Oníṣòwò ń lo òṣùnwọ̀n èkéÓ fẹ́ràn láti rẹ́nijẹ.