Hósíà 9:5-11 BMY

5 Kí ni ẹ̀yin ó ṣe ní ọjọ́ àsè yín tí a ti yànní àwọn ọjọ́ àjọ̀dún Olúwa?

6 Bí wọ́n tilẹ̀ yọ́ kúrò lọ́wọ́ ìparunÉjíbítì yóò kó wọn jọ,Mémúfísì yóò sì sin wọ́n.Ibi ìsọjọ̀ sílífa wọn ni yèrèpè yóò jogún,Ẹ̀gún yóò bo àpótí ìṣúra fàdákà wọn.Ẹ̀gún yóò sì bogbogbo àgọ́ wọn.

7 Àwọn ọjọ́ ìjìyà ń bọ̀;Àwọn ọjọ́ ìṣirò iṣẹ́ ti déJẹ́ kí Ísírẹ́lì mọ èyíNítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ìkórìíra yín sì pọ̀ gan an ni.A ka àwọn wòlíì sí òmùgọ̀A ka ẹni ìmísí sí asínwín.

8 Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run,ni olùṣọ́ ọ Éfúráímù.Ṣíbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀

9 Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ GíbíàỌlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọnyóò sì jẹ wọ́n níyà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

10 “Nígbà tí mo rí Ísírẹ́lì,Ó dàbí ìgbà tí ènìyàn rí èso àjàrà ní ilẹ̀ aṣálẹ̀Nígbà tí mo rí àwọn baba yín.Ó dàbí ìgbà tí ènìyàn rí àkọ́so èso lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ Baali-PéórìWọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá niwọ́n di aláìmọ́ bí ohun tí wọ́n fẹ́ràn.

11 Ògo Éfúráímù yóò fò lọ bí ẹyẹkò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.