28 Ó sì lọ sí Ábídónì, Réóbù, Hámónì àti Kánà títí dé Sídónì ńlá.
29 Ààlà náà sì tẹ̀ sí ìhà Rámà, ó sì lọ sí ìlú olódi Tirè, ó sì yà sí Hósà, ó sì jáde ní òkun ní ilẹ̀ Ákísíbì,
30 Úmà, Áfẹ́kì àti Réóbù. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlélógún àti ìletò wọn.
31 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Áṣíérì, ní agbo ilé agbo ilé.
32 Ìpín kẹfà jáde fún Náfítalì, agbo ilé ní agbo ilé:
33 Ààlà wọn lọ láti Hẹ́lẹ́fì àti igi ńlá ní Sááná nímù; kọjá lọ sí Ádámì Nékébù àti Jábínẹ́ẹ́lì dé Lákúmì, ó sì pín ní Jọ́dánì.
34 Ààlà náà gba ìhà ìwọ̀-oòrùn lọ sí Ásínótì, Tabori ó sì jáde ní Húkókì. Ó sì dé Sébúlúnìe ní ìhà gúsù, Ásíẹ́rì ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Jọ́dánì ní ìhà ìlà-oòrùn.