Jóṣúà 5 BMY

Ìkọlà Fún Ìran Tuntun Ísírẹ́lì? Ìkọlà Ní Gílígálì

1 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba Ámórì ti ìlà-oòrùn Jọ́dánì àti gbogbo àwọn ọba Kénánì tí ń bẹ létí òkun gbọ́ bí Olúwa ti mú Jọ́dánì gbẹ ní iwájú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì títí ti a fi kọjá, ọkàn wọn pámi, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ìgboyà mọ́ láti dojú kọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Jóṣúà pé, “Fi akọ òkúta ṣe abẹ kí o sì kọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ilà ní ìgbà ẹ̀ẹ̀kéjì.”

3 Bẹ́ẹ̀ ni Jóṣúà sì ṣe abẹ akọ òkúta, ó sì kọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ilà, ní Gíbíátì-Hárálótù.

4 Wàyí o, ìdí tí Jóṣúà fi kọ wọ́n nílà nìyìí: Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó ti Éjíbítì jáde wá, gbogbo àwọn ọkùnrin ogun kú ní asálẹ̀ ní ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì.

5 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, gbogbo àwọn ọkùnrin tó jáde láti Éjíbítì ni a ti kọ ní ilà, síbẹ̀ gbogbo ènìyàn tí a bí nínú asálẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n jáde ní Éjíbítì ni wọn kò kọ ní ilà.

6 Àwọn ará Ísírẹ́lì rìn ní ihà fún ogójì (40) ọdún títí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó tó ogun n jà nígbà tí wọ́n kúrò ni Éjíbítì fi kú, nítorí wọn kò gbọ́ràn sí Olúwa. Nítorí Olúwa ti búra fún wọn pé wọn kò ní rí ilẹ̀ tí òun ṣe ìlérí fún àwọn baba wọn láti fí fun wa, ilẹ̀ tí ń ṣàn fún wàrà àti fún oyin.

7 Bẹ́ẹ̀ ni ó gbé àwọn ọmọ wọn dìde dípò wọn, àwọn wọ̀nyí sì ni Jóṣúà kọ ní ilà. Wọ́n wà ní aláìkọlà nítorí a kò tíì kọ wọ́n ní ilà ní ojú ọ̀nà.

8 Lẹ́yìn ìgbà tí gbogbo orílẹ̀ èdè náà kọ ilà tan, wọ́n dúró ní ibi tí wọ́n wà ní ibùdó títí ilà wọn fi jinná.

9 Nígbà náà ní Olúwa wí fún Jóṣúà pé, “Ní òní ni mo yí ẹ̀gàn Éjíbítì kúrò ní orí yín.” Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní Gílígálì títí ó fi di òní yìí.

Àjọ Ìrékọjá Ní Gílígálì.

10 Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹ́rìnlá (14) oṣù náà (oṣù kẹ́rin) (4) nígbà tí wọ́n pàgọ́ ní Gílígálì ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jẹ́ríkò, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì ṣe ọdún Àjọ-ìrékọjá.

11 Ní ọjọ́ kéjì Àjọ-ìrékọjá, ní ọjọ́ náà gan-an ni, wọ́n jẹ nínú; àwọn irè oko ilẹ̀ náà: àkàrà aláìwú, àti ọkà yíyan.

12 Mánà náà sì tan ní ọjọ́ kéjì tí wọ́n jẹ oúnjẹ tí ilẹ̀ náà mú jáde; kò sì sí mánà kankan mọ́ fún àwọn ará Ísírẹ́lì, ṣùgbọ́n ní ọdún náà wọ́n jẹ irè oko ilẹ̀ Kénánì.

Odi Jẹ́ríkò Wó Lulẹ̀

13 Nígbà tí Jóṣúà sún mọ́ Jẹ́ríkò, ó wo òkè ó sì rí ọkùnrin kan tí ó dúró ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú idà ní ọwọ́ rẹ̀. Jóṣúà sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bi í pé, “Ǹjẹ́ ìwọ wà fún wa tàbí fún ọ̀ta a wa?”

14 “Kì í ṣe fún èyíkéyìí ó fèsì, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí olórí ogun Olúwa ni mo wá nísinsin yìí.” Nígbà náà ni Jóṣúà sì wólẹ̀ ní iwájú u rẹ̀ ní ìbẹ̀rù, ó sì bi í léèrè, “Kí ni Olúwa ní í sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀?”

15 Olórí ogun Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹṣẹ̀ rẹ, nítorí pé ibi tí ìwọ dúró sí yìí, ilẹ̀ mímọ́ ni.” Jóṣúà sì ṣe bẹ́ẹ̀.

orí

1 2 3 4 5 6 7 8 9 10 11 12 13 14 15 16 17 18 19 20 21 22 23 24