13 “Lọ, ya àwọn ènìyàn náà sí mímọ́. Sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ fún ọ̀la, nítorí báyìí ni Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí: Ohun ìyàsọ́tọ̀ kan ń bẹ ní àárin yín, Ìwọ Ísírẹ́lì. Ẹ̀yin kì yóò lè dúró níwájú àwọn ọ̀ta a yín títí ẹ̀yin yóò fi mú kúrò.