27 Ǹjẹ́ ó ha yẹ kí àwa tún gbọ́ báyìí pé ẹ̀yin náà tún ń ṣe àwọn nǹkan tí ó burú jọjọ wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣe aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjòjì?”
28 Ọ̀kan lára àwọn ọmọ Jóíádà, ọmọ Élíásíbù olórí àlùfáà jẹ́ àna (o fẹ ọmọbìnrin) Ṣáńbálátì ará a Hórónì. Mo sì lé e jáde kúrò lọ́dọ̀ mi.
29 Rántí, Ọlọ́run mi, nítorí wọ́n ti ba iṣẹ́ àlùfáà jẹ́ pẹ̀lú u májẹ̀mu iṣẹ́ àlùfáà àti ti àwọn Léfì.
30 Nítorí náà, mo ya àwọn àlùfáà àti àwọn Léfì sí mímọ́ kúrò nínú un gbogbo ohun àjòjì, mo sì yan iṣẹ́ fún wọn, olúkúlùkù sí ẹnu iṣẹ́ẹ rẹ̀
31 Mo sì tún pèṣè fún ọrẹ, igi—pákó ní àkókò tí a yàn àti fún àwọn èso àkọ́so.Rántíì mi fún rere, Ọlọ́run mi.