7 Nítorí náà, gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí Mímọ́ ti wí,“Lónìí, bí ẹ bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
8 ẹ má ṣe agídí, gẹ́gẹ́ bíi ti àkókò ìṣọ̀tẹ̀,ní àkókò ìdánwò ninu aṣálẹ̀,
9 nígbà tí àwọn baba-ńlá yín dán mi wò,tí wọ́n fi rí iṣẹ́ mi fún ogoji ọdún.
10 Nítorí náà, mo bínú sí ìran wọn.Mo ní, ‘Nígbà gbogbo ni wọ́n máa ń ṣìnà ní ọkàn wọn.Iṣẹ́ mi kò yé wọn.’
11 Ni mo bá búra pẹlu ibinu,pé wọn kò ní dé ibi ìsinmi mi.”
12 Ẹ kíyèsára, ará, kí ó má ṣe sí ẹnikẹ́ni ninu yín tí yóo ní inú burúkú tóbẹ́ẹ̀ ti kò ní ní igbagbọ, tí yóo wá pada kúrò lẹ́yìn Ọlọrun alààyè.
13 Ṣugbọn ẹ máa gba ara yín níyànjú lojoojumọ níwọ̀n ìgbà tí ọ̀rọ̀ “Òní” tí Ìwé Mímọ́ sọ bá ti bá àwa náà wí, kí ẹ̀ṣẹ̀ má baà tan ẹnikẹ́ni lọ, kí ó sì mú kí ó ṣe agídí sí Ọlọrun.