16 Àwọn àgbààgbà mẹrinlelogun tí wọ́n jókòó lórí ìtẹ́ wọn níwájú Ọlọrun bá dojúbolẹ̀, wọ́n júbà Ọlọrun.
17 Wọ́n ní,“A fi ìyìn fún ọ, Oluwa, Ọlọrun Olodumare,ẹni tí ó wà, tí ó ti wà,nítorí o ti gba agbára ńlá rẹ, o sì ń jọba.
18 Inú àwọn orílẹ̀-èdè ru,ṣugbọn àkókò ibinu rẹ dé,ó tó àkókò láti ṣe ìdájọ́ àwọn òkú,ati láti fi èrè fún àwọn iranṣẹ rẹ, àwọn wolii, àwọn eniyan rẹ,ati àwọn tí ó bẹ̀rù orúkọ rẹ, ìbáà ṣe àwọn mẹ̀kúnnù tabi àwọn eniyan ńláńlá.Àkókò dé láti pa àwọn tí ó ń ba ayé jẹ́ run.”
19 Tẹmpili Ọlọrun ti ṣí sílẹ̀ ní ọ̀run, tí a fi lè rí àpótí majẹmu ninu rẹ̀. Mànàmáná wá bẹ̀rẹ̀ sí kọ, ààrá ń sán, ilẹ̀ ń mì tìtì; yìnyín sì bẹ̀rẹ̀ sí bọ́ sílẹ̀.