2 Kíróníkà 8:12-18 BMY

12 Lórí pẹpẹ Olúwa tí ó ti kọ́ níwájú ìloro náà, Sólómónì sì rú ẹbọ ọrẹ sísun sí Olúwa,

13 Nípa ìlànà ojojúmọ́ fún ẹbọ rírú tí a pa lásẹ láti ọ̀dọ̀ Mósè wá fún ọjọ́ ìsinmi, oṣù tuntun àti lẹ́rìn mẹ́ta lọ́dún, ní àjọ àkàrà àìwú, ní àjọ ọ̀ṣẹ̀ méje àti àjọ ìpàgọ́.

14 Ní pípamọ́ pẹ̀lú ìlànà baba rẹ̀ Dáfídì, ó sì yan ipa àwọn àlùfáà fún iṣẹ́ wọn àti àwọn ọmọ Léfì láti jẹ́ adarí láti máa yin àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ àwọn àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìlànà ojojúmọ́. Ó sì tún yàn àwọn olùsọ́nà nípa pípín sí olúkúlùkù ẹnu ọ̀nà, nítorí èyí ni Dáfídì ènìyàn Ọlọ́run ti paláṣẹ.

15 Wọn kò sì yà kúrò nínú àṣẹ ọba sí àwọn àlùfáà tàbí sí àwọn ọmọ Léfì, sí òràn kọ̀ọ̀kan, àti pẹ̀lú ti ìṣúra.

16 Gbogbo iṣẹ́ Sólómónì ni a gbé jáde láti ọjọ́ ìfi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lé lẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ ìparí. Bẹ́ẹ̀ ni ilé Olúwa sì parí.

17 Nígbà náà ni Sólómónì lọ sí Ésíónì Gébérì àti Élótì àti sí etí òkun Édómù.

18 Húrámù sì fi ọ̀kọ̀ ránsẹ́ sì i nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin tí ó mòye òkun. Èyí pẹ̀lú àwọn ènìyàn Sólómónì, lọ sí Ófírì wọ́n sì gbé àádọ́ta irinwó tálẹ́ntì wúrà wá, padà èyí tí wọ́n sì mú tọ ọba Sólómónì wá.