Ẹ́sítà 1:11-17 BMY

11 Kí wọn mú ayaba Fásítì wá ṣíwájúu rẹ̀, ti òun ti adé ọba rẹ̀, kí ó lè wá fi ẹwà rẹ̀ hàn àwọn ènìyàn àti àwọn ọlọ́lá, nítorí tí ó rẹwà.

12 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ jẹ́ iṣẹ́ ọba, ayaba Fásítì kọ̀ láti wá. Nígbà náà ni ọba bínú gidgidi, ìbínú náà sì pọ̀ jọjọ.

13 Gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀ ní ìgbà gbogbo, ọba máa ń béèrè ọ̀rọ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ó ní ìmọ̀ òfin àti ìdájọ́, ó sọ ọ́ fún àwọn amòye tí wọ́n mòye àkókò,

14 àwọn tí wọ́n súnmọ́ ọba àwọn wọ̀nyí ni Káríṣénà, Ṣétarì, Ádímátà, Tárísísì, Mérésì, Márísénà àtí Mémúkánì, àwọn ọlọ́lá méje ti Páṣíà àti Médíà tí wọ́n ṣe pàtàkì sí ọba, wọ́n sì tún wà ní ibi gíga ní ìjọba.

15 Ó béèrè pé, “Kí ni a lè ṣe sí ayaba Fásítì gẹ́gẹ́ bí òfin? Nítorí kò tẹríba fún àṣẹ ọba Ṣérísésì tí àwọn ìwẹ̀fà ọba sọ fún un.”

16 Mémúkánì sì dáhùn níwájú ọba àti àwọn ọlọ́lá pé, “Ayaba Fásítì ti ṣe búburú, kì í ṣe sí ọba nìkan Ṣùgbọ́n sí gbogbo àwọn ọlọ́lá àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní gbogbo agbégbé ilẹ̀ ọba Ṣérísésì.

17 Nítorí ìwà ayaba yìí yóò tàn dé ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn obínrin, tó bẹ́ẹ̀ tí ọkọ wọn yóò di gígàn lójúu wọn, wọn yóò sì sọ pé, ọba Ṣérísésì pàṣẹ̀ pé kí á mú ayaba Fásítì wá ṣíwájú òun, ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti wá.