Jónà 1 BMY

Jónà Sá Ní Iwájú Olúwa

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jónà ọmọ Ámítaì wá, wí pé:

2 “Dìde lọ sí ìlú ńlá Nínéfè kí o sì wàásù sí i, nítorí ìwà búburú rẹ̀ gòkè wá iwájú mi.”

3 Ṣùgbọ́n Jónà dìde kúrò láti sá lọ sí Tásísì kúrò níwájú Olúwa, ó sì ṣọ̀kalẹ̀ lọ sí Jópà, ìbí ti ó tí rí ọkọ̀ kan tí ń lọ sí Tásísì: lẹ́yìn ti ó sanwó ọkọ̀, ó wọlé sínú rẹ̀, láti bá wọn lọ sí Tásísì kúrò níwájú Olúwa.

4 Nígbà náà ni Olúwa rán ìjì ńlá jáde sí ojú òkun, ìjì líle sì wà nínú òkun tóbẹ́ẹ̀ tí ọkọ̀ náà dàbí ẹni pé yóò fọ́.

5 Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ bẹ̀rù, olúkúlùkù sì ń kígbe sí ọlọ́run rẹ̀, wọ́n kó ẹrù tí ó wà nínú ọkọ̀ dà sínú òkun, kí ó bá à lè fúyẹ́.Ṣùgbọ́n Jónà sọ̀kalẹ̀ lọ sí ẹ̀gbẹ́ ọkọ̀ ó sì dùbúlẹ̀, ó sùn wọra.

6 Bẹ́ẹ̀ ni olórí ọkọ̀ tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi sùn, ìwọ olóorun? Dìde kí o ké pe Ọlọ́run rẹ! Bóyá yóò ro tiwa, kí àwa má ba à ṣègbé.”

7 Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ sọ fún ara wọn pé, “Wá, ẹ jẹ́ kí a sẹ́ kèké, kí àwa kí o le mọ̀ nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa.” Wọ́n ṣẹ́ kèké, kèké sì mú Jónà.

8 Nígbà náà ni wọn wí fún un pé, “Sọ fún wa, àwa bẹ̀ ọ́, nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa? Kí ni iṣẹ́ rẹ? Níbo ni ìwọ ti wá? Kí ni orúkọ ìlú rẹ? Ẹ̀yà orílẹ̀-èdè wo sì ni ìwọ sì í ṣe?”

9 Òun sì dá wọn lóhùn pé, “Hébérù ni èmi, mo sì bẹ̀rù Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run ẹni tí ó dá òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀.”

10 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù gidigidi, wọn sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ṣe èyí?” (Nítorí àwọn ọkùnrin náà mọ̀ pé ó ń sá kúrò ní iwájú Olúwa ni, nítorí òun ti sọ fun wọn bẹ́ẹ̀.)

11 Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Kí ni kí àwa ó se sí ọ kí òkun lè dákẹ́ fún wa?” Nítorí òkun ru, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle.

12 Òun sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé mi, kí ẹ sì sọ mi sínú òkun, bẹ́ẹ̀ ni okun yóò sì dákẹ́ fún un yin. Nítorí èmi mọ̀ pé, nítorí mi ni ẹ̀fúùfù líle yìí ṣe dé bá a yín.”

13 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà wà á kíkan láti mú ọkọ̀ wà sí ilẹ̀: ṣùgbọ́n wọn kò lè ṣe é: nítorí tí òkun túbọ̀ ru síi, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle sí wọn.

14 Nítorí náà wọ́n kígbe sí Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Olúwa àwa bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí àwa ṣègbé nítorí ẹ̀mí ọkùnrin yìí. Má sì ka ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sí wa ní ọrùn, nítorí ìwọ, Olúwa, ti ṣe bí ó ti wù ọ́.”

15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé Jónà, tí wọ́n sì sọ ọ́ sínú òkun, òkun sì dẹ́kun ríru rẹ̀.

16 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù Olúwa gidigidi, wọn si rúbọ sí Olúwa, wọ́n sì jẹ́ ẹ̀jẹ́.

17 Ṣùgbọ́n Olúwa ti pèṣè ẹja ńlá kan láti gbé Jónà mì. Jónà sì wà nínú ẹja náà ni ọ̀sán mẹ́ta àti òru mẹ́ta.

orí

1 2 3 4