Nehemaya 5:9-15 BM

9 Mo wá sọ pé, “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe kò dára. Ǹjẹ́ kò yẹ kí ẹ máa fi ìbẹ̀rù rìn ní ọ̀nà Ọlọrun, kí àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ́ ọ̀tá wa má baà máa kẹ́gàn wa?

10 Pàápàá tí ó jẹ́ pé èmi ati àwọn arakunrin mi ati àwọn iranṣẹ mi ni à ń yá wọn ní owó ati oúnjẹ. Ẹ má gba èlé lọ́wọ́ wọn mọ́, ẹ sì jẹ́ kí á pa gbèsè wọn rẹ́.

11 Ẹ dá ilẹ̀ oko wọn pada fún wọn lónìí, ati ọgbà àjàrà wọn, ati ọgbà igi olifi wọn, ati ilé wọn, ati ìdá kan ninu ọgọrun-un owó èlé tí ẹ gbà, ati ọkà, waini, ati òróró tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn.”

12 Wọ́n sì dáhùn pé, “A óo dá gbogbo rẹ̀ pada, a kò sì ní gba nǹkankan lọ́wọ́ wọn mọ́. A óo ṣe bí o ti wí.”Mo bá pe àwọn alufaa, mo sì mú kí wọ́n jẹ́jẹ̀ẹ́ láti ṣe ohun tí wọ́n ṣèlérí pé àwọn yóo ṣe.

13 Mo gbọn àpò ìgbànú mi, mo ní, “Báyìí ni Ọlọrun yóo gbọn gbogbo ẹni tí kò bá mú ẹ̀jẹ́ yìí ṣẹ kúrò ninu ilé rẹ̀ ati kúrò lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀. Ọlọrun yóo gbọn olúwarẹ̀ dànù lọ́wọ́ òfo.”Gbogbo àwọn tí wọ́n wà ní àpéjọpọ̀ náà sì ṣe “Amin”, wọ́n sì yin OLUWA. Àwọn eniyan náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ.

14 Siwaju sí i, láti ìgbà tí a ti yàn mí sí ipò gomina ní ilẹ̀ Juda, láti ogun ọdún tí Atasasesi ti jọba sí ọdún kejilelọgbọn, èmi ati arakunrin mi kò jẹ oúnjẹ tí wọ́n yà sọ́tọ̀ fún wa gẹ́gẹ́ bíi gomina.

15 Àwọn gomina yòókù tí wọ́n jẹ ṣiwaju mi a máa ni àwọn eniyan lára, wọn a máa gba oúnjẹ mìíràn ati ọtí waini lọ́wọ́ wọn, yàtọ̀ sí ogoji ìwọ̀n Ṣekeli fadaka tí wọn ń gbà. Àwọn iranṣẹ wọn pàápàá a máa ni àwọn eniyan lára. Ṣugbọn, nítèmi, n kò ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí pé mo bẹ̀rù Ọlọrun.