2 Bí òdòdó lílì ti rí láàrin ẹ̀gún,ni olólùfẹ́ mi rí láàrin àwọn ọmọge.
3 Bí igi ápù ti rí láàrin àwọn igi igbó,ni olùfẹ́ mí rí láàrin àwọn ọmọkunrin.Pẹlu ìdùnnú ńlá ni mo fi jókòó lábẹ́ òjìji rẹ̀,èso rẹ̀ sì dùn lẹ́nu mi.
4 Ó mú mi wá sí ilé àsè ńlá,ìfẹ́ ni ọ̀págun rẹ̀ lórí mi.
5 Fún mi ni èso àjàrà gbígbẹ jẹ,kí ara mi mókun,fún mi ní èso ápù jẹ kí ara tù mí,nítorí pé, àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mí.
6 Ó wù mí kí ọwọ́ òsì rẹ̀ wà ní ìgbèrí mi,kí ó sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ fà mí mọ́ra.
7 Mo kìlọ̀ fun yín, ẹ̀yin ọmọbinrin Jerusalẹmu,ní orúkọ egbin, ati ti àgbọ̀nrín pé,ẹ kò gbọdọ̀ jí ìfẹ́ títí yóo fi wù ú láti jí.
8 Mo gbọ́ ohùn olùfẹ́ mi, wò ó! Ó ń bọ̀,ó ń fò lórí àwọn òkè ńlá,ó sì ń bẹ́ lórí àwọn òkè kéékèèké.