48 Ọlọrun ti jẹ́ kí n gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi,ó ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba lábẹ́ mi;
49 ó sì fà mí yọ lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.“OLUWA, ìwọ ni o gbé mi ga ju àwọn ọ̀tá mi lọ,o sì dáàbò bò mí, lọ́wọ́ àwọn oníwà ipá.
50 Nítorí náà, n óo máa yìn ọ́ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè,n óo máa kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ.
51 Ọlọrun fi ìṣẹ́gun ńlá fún ọba rẹ̀,ó sì fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ han ẹni tí ó fi àmì òróró yàn,àní Dafidi ati arọmọdọmọ rẹ̀ laelae!”