36 “Olùkọ́ni, òfin wo ni ó ṣe pataki jùlọ ninu Ìwé Òfin?”
37 Jesu dá a lóhùn pé, “ ‘Fẹ́ Oluwa Ọlọrun rẹ pẹlu gbogbo ọkàn rẹ, ati gbogbo ẹ̀mí rẹ, ati ní gbogbo èrò rẹ.’
38 Èyí ni òfin tí ó ga jùlọ, òun sì ni ekinni.
39 Ekeji fi ara jọ ọ́: ‘Fẹ́ràn ọmọnikeji rẹ bí o ti fẹ́ ara rẹ.’
40 Òfin mejeeji wọnyi ni gbogbo òfin ìyókù ati ọ̀rọ̀ inú ìwé àwọn wolii rọ̀ mọ́.”
41 Nígbà tí àwọn Farisi péjọ pọ̀, Jesu bi wọ́n pé,
42 “Kí ni ẹ rò nípa Mesaya, ọmọ ta ni?”Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ọmọ Dafidi ni.”