38 Èyí ni òfin tí ó ga jùlọ, òun sì ni ekinni.
39 Ekeji fi ara jọ ọ́: ‘Fẹ́ràn ọmọnikeji rẹ bí o ti fẹ́ ara rẹ.’
40 Òfin mejeeji wọnyi ni gbogbo òfin ìyókù ati ọ̀rọ̀ inú ìwé àwọn wolii rọ̀ mọ́.”
41 Nígbà tí àwọn Farisi péjọ pọ̀, Jesu bi wọ́n pé,
42 “Kí ni ẹ rò nípa Mesaya, ọmọ ta ni?”Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ọmọ Dafidi ni.”
43 Ó bá tún bi wọ́n pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, báwo ni Ẹ̀mí Mímọ́ ṣe darí Dafidi tí Dafidi fi pe Mesaya ní ‘Oluwa’? Dafidi sọ pé,
44 ‘OLUWA sọ fún Oluwa mi pé:Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mitítí n óo fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di ohun ìtìsẹ̀ rẹ.’