13 Ibojì tí ó yanu sílẹ̀ ni ọ̀nà ọ̀fun wọn,ẹ̀tàn kún ẹnu wọn;oró paramọ́lẹ̀ wà létè wọn;
14 ẹnu wọn kún fún èpè ati ọ̀rọ̀ burúkú.
15 Ẹsẹ̀ wọn yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.
16 Ọ̀nà jamba ati òṣì ni wọ́n ń rìn.
17 Wọn kò mọ ọ̀nà alaafia.
18 Kò sí ìbẹ̀rù Ọlọrun ní ọkàn wọn.”
19 A mọ̀ pé ohunkohun tí Òfin bá wí, ó wà fún àwọn tí ó mọ Òfin ni, kí ẹnikẹ́ni má ṣe rí àwáwí wí, kí gbogbo aráyé lè wà lábẹ́ ìdájọ́ Ọlọrun.