8 Ṣé, “Kí á kúkú máa ṣe ibi kí rere lè ti ibẹ̀ jáde?” Bí àwọn onísọkúsọ kan ti ń sọ pé à ń sọ. Irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ yẹ fún ìdálẹ́bi.
9 Kí ni kí á rí dìmú ninu ọ̀rọ̀ yìí? Ṣé àwa Juu sàn ju àwọn orílẹ̀-èdè yòókù lọ ni? Rárá o! Nítorí a ti wí ṣáájú pé ati Juu ati Giriki, gbogbo wọn ni ó wà ní ìkáwọ́ ẹ̀ṣẹ̀.
10 Ó wà ní àkọsílẹ̀ bẹ́ẹ̀ pé,“Kò sí ẹnìkan tí ó jẹ́ olódodo; kò sí ẹnìkankan.
11 Kò sí ẹni tí òye yé,kò sí ẹni tí ó ń wá Ọlọrun.
12 Gbogbo wọn ti yapa kúrò lójú ọ̀nà,gbogbo wọn kò níláárí mọ́,kò sí ẹni tí ó ń ṣe rere,kò sí ẹnìkan.
13 Ibojì tí ó yanu sílẹ̀ ni ọ̀nà ọ̀fun wọn,ẹ̀tàn kún ẹnu wọn;oró paramọ́lẹ̀ wà létè wọn;
14 ẹnu wọn kún fún èpè ati ọ̀rọ̀ burúkú.