7 Ní ọjọ́ náà Dáfídì kọ́kọ́ fi lé Ásáfù àti àwon ẹlẹgbẹ́ Rẹ̀ lọ́wọ́ orin Dáfídì ti ọpẹ́ sí Olúwa:
8 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ Rẹ̀,ẹ fi iṣẹ́ Rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe
9 Ẹ kọrin síi, ẹ kọrin ìyìn, síi,Ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀
10 Ìyìn nínú orúkọ Rẹ̀ mímọ́;jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.
11 Ẹ wá Olúwa àti agbára Rẹ̀;O wá ojú Rẹ̀ nígbà gbogbo.
12 Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe,isẹ́ ìyanu Rẹ̀ àti ídájọ́ tí Ó ti sọ.
13 A! èyin ìran ọmọ Ísírẹ́lì ìránṣẹ́ Rẹ̀,àwon ọmọ Jákọ́bù, ẹ̀yin tí ó ti yàn.