29 Lẹ́gbẹ̀ ìpínlẹ̀ ti Mánásè ni Bétí ṣánì, Tánákì, Mógídò àti Dórì lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìletò Rẹ̀. Àwọn ìran ọmọ Jóṣẹ́fù ọmọ Ísírẹ́lì ń gbé nínú ìlú wọ̀nyí.
30 Àwọn ọmọ Ásérì:Ímíná, Ísúa, Ísúáì àti Béríá. Arábìnrin wọn sì jẹ́ Ṣérà.
31 Àwọn ọmọ Béríá:Hébérì àti Málíkíélì, tí ó jẹ́ baba Bírísáítì.
32 Hébérì jẹ́ baba Jáfílétì, Ṣómérì àti Hótamì àti ti arábìnrin wọn Ṣúà.
33 Àwọn ọmọ Jáfílétì:Pásákì, Bímíhátì àti Ásífátì.Wọ̀n yí ni àwọn ọmọ Jáfílétì.
34 Àwọn ọmọ Ṣómérì:Áhì, Rógà, Jáhúbà àti Árámù.
35 Àwọn ọmọ arákùnrin Rẹ̀ HélémùṢófà, Ímínà, Ṣélésì àti Ámálì.