10 Ìbẹ̀rù Olúwa bà lórí gbogbo ìjọba ilẹ̀ tí ó yí Júdà ká, débi pé wọn kò bá Jéhóṣáfátì jagun.
11 Lára àwọn ará Fílístínì, mú ẹ̀bùn fàdákà gẹ́gẹ́ bí owó ọba wá fún Jéhóṣáfátì, àwọn ará Árábíà sì mú ọ̀wọ́ ẹran wá fún-un, ẹgbàrin ó dín ọ̀dúnrún àgbò àti ẹgbarìndín ní ọ̀ọ́dúnrún òbúkọ.
12 Jéhóṣáfátì sì ń di alágbára nínú agbára síi, ó sì kọ́ ilé olódi àti ilé ìsúra púpọ̀ ní Júdà
13 Ó sì ní ìṣúra ní ìlu Júdà. Ó sì tún ní àwọn alágbára jagunjagun akọni ọkùnrin ní Jérúsálẹ́mù.
14 Iye wọn gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn nì wọ̀nyí:Láti Júdà, àwọn olórí ìsùkan ti ẹgbẹ̀rún (1,000):Ádínà olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀dó gún alágbára akọni ọkùrin (300, 00);
15 Èkejì Jéhósáfátì olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá ọkùnrin (280,000);
16 Àtẹ̀lé Ámásíà ọmọ Síkírì, ẹni tí ó fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ Olúwa pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá (200,000).