2 Kíróníkà 35:18-24 BMY

18 Àjọ ìrékọjá náà kòsì tí ì sí èyí tí ó dàbí i rẹ̀ ní Ísírẹ́lì títí dé ọjọ́ wòlíì Sámúẹ́lì, kò sì sí ọ̀kan lára àwọn ọba Ísírẹ́lì tí ó pa irú àjọ ìrékọjá bẹ́ẹ̀ mọ́ gẹ́gẹ́ bí Jósíà ti se, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àwọn ọmọ Léfì àti gbogbo àwọn Júdà àti Ísírẹ́lì tí ó wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ènìyàn Jérúsálẹ́mù.

19 Àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí ní ọdún kejìdínlogún ìjọba Jósíà

20 Lẹ́yìn gbogbo èyí nígbà tí Jósíà ti tún ilẹ̀ náà se tán, Nékò ọba Éjíbítì gòkè lọ láti bá Keríkemísì jà lórí odo Éúfírátè, Jósíà sì jáde lọ láti pàdé rẹ̀ ní ibi ìjà.

21 Ṣùgbọ́n Nékò rán ìránṣẹ́ sí i wí pé, “Ìjà wo ni ó ń bẹ láàrin èmi àti ìwọ, ọba Júdà? Kìí se ìwọ ni èmi tọ̀ wá ní àkókò yìí, ṣùgbọ́n, ilé pẹ̀lú èyí ti mo bá níjà. Ọlọ́run ti sọ fún mi láti yára àti láti dúró nípa ṣíṣe ìdènà Ọlọ́run, ẹni tí ó wà pẹ̀lú mi, kí òun má bàá pa ọ́ run.”

22 Jósíà, bí ó ti wù kí ó rí, ẹni tí kò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó pa ara rẹ̀ dà kí ó le báa jà, kí ó ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin Ọlọ́run ṣùgbọ́n ó lọ láti jà lórí àfonífojì Mégídò.

23 Tafàtafà sì ta ọfà sí ọba Jósíà, ó sì sọ fún àwọn ìjòyè pé, “Ẹgbé mi kúrò, èmi sì ti gba ọgbẹ́ gidigidi.”

24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbé e jáde kúrò nínú kẹ̀kẹ́ náà, wọ́n sì gbé e sínú kẹ̀kẹ́ mìíràn, wọ́n sì gbé e wá sí Jérúsálẹ́mù, níbi tí ó ti kú, wọ́n sì sin ín sínú ọ̀kan nínú àwọn ibojì àwọn baba rẹ̀, gbogbo Júdà àti gbogbo Jérúsálẹ́mù sì sọ̀fọ̀ fún un.