2 Sámúẹ́lì 18:14-20 BMY

14 Jóábù sì wí pé, “Èmi kì yóò dúró bẹ́ẹ̀ níwájú rẹ.” Ó sì mú ọ̀kọ̀ mẹ́ta lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì fi wọ́n gún Ábúsálómù ní ọkàn, nígbà tí ó sì wà láàyè ní agbede-méjì igi óákù náà.

15 Àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin mẹ́wàá tí ó máa ń ru ìhámọ́ra Jóábù sì yí Ábúsálómù ká, wọ́n sì kọlù ú, wọ́n sì pa á,

16 Jóábù sì fun ìpè, àwọn ènìyàn náà sì yípadà láti máa lépa Ísírẹ́lì: nítorí Jóábù ti pe àwọn ènìyàn náà padà.

17 Wọ́n sì gbé Ábúsálómù, wọ́n sì sọ ọ́ sínú ihò ńlá kan ní igbó náà, wọ́n sì kó òkúta púpọ̀ jọ sí i lórí, gbogbo Ísírẹ́lì sì sá, olúkúlùkù sí inú àgọ́ rẹ̀.

18 Ábúsálómù ní ìgbà ayé rẹ̀, sì mọ ọ̀wọ̀n kan fún ara rẹ̀, tí ń bẹ ní àfonífojì ọba: nítorí tí ó wí pé, Èmi kò ní ọmọkùnrin tí yóò pa orúkọ mi mọ́ ní ìrántí: òun sì pe ọ̀wọ̀n náà nípa orúkọ rẹ̀: a sì ń pè é títí di òní, ní ọ̀wọ́n Ábúsálómù.

19 Áhímásì ọmọ Sádókù sì wí pé, “Jẹ́ kí èmi ó súré nísinsin yìí, kí èmi sì mú ìhìn tọ ọba lọ, bí Olúwa ti gbẹ̀san rẹ̀ lára àwọn ọ̀ta rẹ̀.”

20 Jóábù sì wí fún un pé, “Ìwọ kì yóò mù ìhìn lọ lónìí, ṣùgbọ́n ìwọ ó mú lọ ní ijọ́ mìíràn: ṣùgbọ́n lónìí yìí ìwọ kì yóò mú ìhìn kan lọ, nítorí tí ọmọ Ọba ṣe aláìsí.”