Ẹ́sítà 3:1-7 BMY

1 Lẹ́yìn àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí, ọba Ṣérísésì dá Hámánì ọmọ Hámádátà, ará a Ágágì lọ́lá, ọba gbé e ga, ó si fún un ní àga ọlá tí ó ju ti gbogbo àwọn ọlọ́lá tó kù lọ.

2 Gbogbo àwọn ìjòyè ọba tí ó wà lẹ́nu ọ̀nà ọba wọn kúnlẹ̀ wọ́n sì fi ọlá fun Hámánì, nítorí ọba ti pàṣẹ èyí nípa tirẹ̀. Ṣùgbọ́n Modékáì kò ní kúnlẹ̀ tàbí bu ọlá fún-un.

3 Nígbà náà ni àwọn ìjòyè ọba tí ó wà ní ẹnu ọ̀nà béèrè lọ́wọ́ Módékáì pé, “È éṣe tí ìwọ kò ṣe pa àṣẹ ọba mọ́.”

4 Ní ojoojúmọ́ ni wọ́n máa n sọ fún-un ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti ṣe bẹ́ẹ̀. Nítorí náà, wọ́n sọ fún Hámánì nípa rẹ̀ láti wòó bóyá ó lè gba irú ìwà tí Módékáì ń hù yìí, nítorí tí ó ti sọ fún wọn pé Júù ni òun.

5 Nígbà tí Hámánì ríi pé Módékáì kò ní kúnlẹ̀ tàbí bu ọlá fún òun, ó bínú.

6 Síbẹ̀ kò mọ irú ènìyàn tí Módékáì jẹ́, ó kẹ́gàn àti pa Módékáì nìkan. Dípò bẹ́ẹ̀ Hámánì ń wá láti pa gbogbo ènìyàn Módékáì run, àwọn Júù jákèjádò gbogbo ìjọba Ṣérísésì.

7 Ní ọdún kejìlá ọba Ṣérísésì, ní oṣù kìn-ín-ní, èyí ni oṣù nísánì, wọ́n da Púrì (èyí tí í ṣe, ìbò) ní iwájú Hámánì láti yan ọjọ́ kan àti oṣù, ìbò náà sì wáyé ní oṣù kejìlá, oṣù Ádárì.