5 wọ́n sì pa àwọn bí mẹ́rìndínlógójì nínú wọn. Wọ́n sì ń lépa àwọn ará Ísírẹ́lì láti ibodè ìlú títí dé Ṣébárímù, wọ́n sì pa àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀. Àyà àwọn ènìyàn náà sì já, ọkàn wọn sì pámi.
6 Jósúà sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dojú bolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa títí di àṣálẹ́. Àwọn àgbà Ísírẹ́lì sì ṣe bákan náà, wọ́n ku eruku sí orí i wọn.
7 Jósúà sì wí pé, “Háà, Olúwa Ọlọ́run alágbára, nítorí i kiín ni ìwọ ṣe mú àwọn ènìyàn yìí kọjá a Jọ́dánì, láti fi wọ́n lé àwọn ará Ámórì lọ́wọ́; láti pa wọn run? Àwa ìbá mọ̀ kí a dúró ní òdì kéjì Jọ́dánì?
8 Olúwa, kín ni èmi yóò sọ nísinsin yìí tí Ísírẹ́lì sì ti sá níwájú ọ̀ta a rẹ̀.?
9 Àwọn Kénánì àti àwọn ènìyàn ìlú tí ó kù náà yóò gbọ́ èyí, wọn yóò sì yí wa ká, wọn yóò sì ké orúkọ wa kúrò ní ayé. Kí ni ìwọ ó ha ṣe fún orúkọ ńlá à rẹ?”
10 Olúwa sì sọ fún Jóṣúà pé, “Dìde! Kín ni ìwọ ń ṣe tí ó fi dojú bolẹ̀?
11 Ísírẹ́lì ti ṣẹ̀; Wọ́n sì ti ba májẹ̀mú mi jẹ́, èyí tí mo pàṣẹ fún wọn pé kí wọn pamọ́. Wọ́n ti mú nínú ohun ìyàsọ́tọ̀, wọ́n ti jí, wọ́n pa irọ́, Wọ́n ti fi wọ́n sí ara ohun ìní wọn.