23 Lẹ́yìn wọn ni Bẹ́ńjámínì àti Háṣíbù tún èyí ti iwájú ilé wọn ṣe; lẹ́yìn wọn ni, Ásáríyà ọmọ Máṣéyà ọmọ Ananíyà tún ti ẹ̀gbẹ́ ilé rẹ̀ ṣe.
24 Lẹ́yìn rẹ̀ ni Bínúì ọmọ Hénádádì tún apá mìíràn ṣe, láti ilé Ásáríyà dé orígun àti kọ̀rọ̀,
25 àti Pálálì ọmọ Úṣáì tún ọ̀kánkán orígun ṣe àti ilé ìṣọ́ tí ó yọ sóde láti ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ààfin tòkè lẹ́gbẹ̀ẹ́ agbégbé àwọn olùṣọ́. Lẹ́yìn rẹ̀ ni, Pédáyà ọmọ Párósì
26 àti àwọn ìránṣẹ́ẹ tẹ́ḿpìlì tí ó ń gbé ní òkè Ófélì ṣe àtúnṣe títí dé ibi ọ̀kánkán ibodè omi sí ìhà ìlà oòrùn àti ilé ìṣọ́ tí ó yọ sóde.
27 Lẹ́yìn wọn ni àwọn ènìyàn Tékóà tún apá mìíràn ṣe, láti ilé ìṣọ́ ńlá tí ó yọ sóde títí dé ògiri Ófélì.
28 Àwọn àlùfáà ni ó ṣe àtúnṣe òkè ibodè ẹsin ṣe, ẹnì kọ̀ọ̀kan ní iwájú ilée rẹ̀.
29 Lẹ́yìn wọn, Ṣádókì ọmọ Ímérì tún ọ̀kánkán ilé rẹ̀ ṣe. Lẹ́yìn rẹ̀ ni Ṣémáyà ọmọ Ṣekanáyà, olùṣọ́ ibodè ìhà ìlà oòrùn ṣe àtúnṣe.