1 Àwọn orin tí ó dùn jùlọ tí Solomoni kọ nìwọ̀nyí:
2 Wá fi ẹnu kò mí lẹ́nu,nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ọtí waini lọ.
3 Òróró ìpara rẹ ní òórùn dídùn,orúkọ rẹ dàbí òróró ìkunra tí a tú jáde;nítorí náà ni àwọn ọmọbinrin ṣe fẹ́ràn rẹ.
4 Fà mí mọ́ra, jẹ́ kí á ṣe kíá,ọba ti mú mi wọ yàrá rẹ̀.Inú wa yóo máa dùn, a óo sì máa yọ̀ nítorí rẹa óo gbé ìfẹ́ rẹ ga ju ọtí waini lọ;abájọ tí gbogbo àwọn obinrin ṣe fẹ́ràn rẹ!
5 Ẹ̀yin ọmọbinrin Jerusalẹmu,mo dúdú lóòótọ́, ṣugbọn mo lẹ́wà,mo dàbí àgọ́ Kedari,mo rí bí aṣọ títa tí ó wà ní ààfin Solomoni.
6 Má wò mí tìka-tẹ̀gbin, nítorí pé mo dúdú,oòrùn tó pa mí ló ṣe àwọ̀ mi bẹ́ẹ̀.Àwọn ọmọ ìyá mi lọkunrin bínú sí mi,wọ́n fi mí ṣe olùtọ́jú ọgbà àjàrà,ṣugbọn n kò tọ́jú ọgbà àjàrà tèmi alára.