7 Oluwa pẹlu yio kọ́ tète gba agọ Juda là na, ki ogo ile Dafidi ati ogo awọn ara Jerusalemu ma bà gbe ara wọn ga si Juda.
8 Li ọjọ na li Oluwa yio dãbò bò awọn ti ngbe Jerusalemu; ẹniti o ba si ṣe ailera ninu wọn li ọjọ na yio dabi Dafidi; ile Dafidi yio si dabi Ọlọrun, bi angeli Oluwa niwaju wọn.
9 Yio si ṣe li ọjọ na, emi o wá lati pa gbogbo awọn orilẹ-ède run ti o wá kọjuja si Jerusalemu.
10 Emi o si tú ẹmi ore-ọfẹ ati ẹbẹ sori ile Dafidi ati sori Jerusalemu: nwọn o si ma wò mi ẹniti nwọn ti gún li ọ̀kọ, nwọn o si ma ṣọ̀fọ rẹ̀, gẹgẹ bi enia ti nṣọ̀fọ fun ọmọ ọkunrin rẹ̀ kanṣoṣo, nwọn o si wà ni ibanujẹ, bi ẹniti mbanujẹ fun akọbi rẹ̀.
11 Li ọjọ na li ọ̀fọ nlanlà yio wà ni Jerusalemu, gẹgẹ bi ọ̀fọ Hadadrimmoni li afonifoji Megiddoni.
12 Ilẹ na yio ṣọ̀fọ, idile idile lọtọ̀tọ; idile Dafidi lọ́tọ̀; ati awọn aya wọn lọ́tọ̀; idile Natani lọ́tọ̀, ati awọn aya wọn lọtọ̀.
13 Idile Lefi lọ́tọ̀, ati awọn aya wọn lọ́tọ̀; idile Ṣimei lọ́tọ̀, ati awọn aya wọn lọ́tọ̀.