2 Dáfídì sì mọ Ísírẹ̀lì àti pé Olúwa ti fi òun ṣe ọba lórí Ísírẹ́lì àti pé Ìjọba Rẹ̀ ga jùlọ nítorí ti àwon ènìyàn Rẹ̀.
3 Ní Jérúsálẹ́mù Dáfídì mú ọ̀pọ̀ ìyàwó ó sì di bàbá àwọn ọmọ ọkùnrin púpọ̀ àti ọmọbìnrin.
4 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ náà tí wọ́n bí fún un níbẹ̀: Ṣámúyà, Ṣóbábù, Nátanì, Ṣólómónì,
5 Íbárì, Élíṣúà, Élífélétì,
6 Nógà, Néfégì, Jáfíà,
7 Élísámà, Bélíádà, àti Élífélétì.
8 Nígbà tí àwọn ará Fílístínì gbọ́ pé a ti fi àmì òróró yàn Dáfídì ní ọba lórí gbogbo Ísírẹ́lì, wọ́n sì lọ sókè pẹ̀lú ipá láti wá a rí, ṣùgbọ́n Dáfídì gbọ́ nípa Rẹ̀ ó sì jáde lọ láti pàdé wọn.