14 Ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Nàtaníẹ́lì, ẹlẹ́ẹ̀káàrùn-ún Rádáì,
15 ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Ósémù àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dáfídì.
16 Àwọn arábìnrin wọn ni Ṣérúà àti Ábígáílì. Àwọn ọmọ mẹ́ta Ṣérúà ni Ábíṣáì, Jóábù àti Ásáélì.
17 Ábígáílì ni ìyá Ámásà, ẹni tí baba Rẹ̀ sì jẹ́ Jétérì ará Íṣímáẹ́lì.
18 Kélẹ́bù ọmọ Hésírónì ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó Rẹ̀ Ásúbà (láti ọ̀dọ̀ Jéríótù). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Rẹ̀: Jéṣérì, Ṣóbábù àti Árídónì.
19 Nígbà tí Ásúbà sì kú, Kélẹ́bù sì fẹ́ Éfúrátì ní aya, ẹni tí ó bí Húrì fún un.
20 Húrì ni baba Úrù, Úrù sì jẹ́ baba Bésálélì.