1 Kíróníkà 20:1-6 BMY

1 Ní àkókò àkọ́rọ̀ òjò, ni ìgbà tí àwọn ọba lọ sí ogun, Jóábù ṣamọ̀nà àwọn ọ̀wọ́ ọmọ ogun. Ó fi ilẹ̀ àwọn ará Ámónì ṣòfò. Ó lọ sí ọ̀dọ̀ Rábà. Ó sì fi ogun dúró tì í. Ṣùgbọ́n Dáfídì dúró sí Jérúsálẹ́mù Jóábù kọlu Rábà, ó sì fi sílẹ̀ ní ìparun.

2 Dáfídì mú adé kúrò lórí àwọn ọba wọn ìwọ̀n Rẹ̀ dàbí i talẹ́ńtì wúrà, a sì tò ó jọ pẹ̀lú àwọn òkúta iyebíye. A sì gbé e ka orí Dáfídì. Ó kó ọ̀pọ̀ ìkógun láti ìlú ńlá náà.

3 Ó sì kó gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ jáde, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ láti ṣíṣẹ́ pẹ̀lú ayùn àti ìtulẹ̀ onírin àti àáké. Dáfídì ṣe eléyìí sí gbogbo àwọn ará ìlú Ámónì. Nígbà náà, Dáfídì àti gbogbo àwọn ọmọ ogun Rẹ̀ padà sí Jérúsálẹ́mù.

4 Ní ẹ̀yìn èyí ni ogun bẹ́ sílẹ̀ ní Géṣérì pẹ̀lu àwọn ará Fílístínì, ní àkókò yìí ni Ṣíbékíà ará Húsà pa Ṣípáì, ọ̀kan lára àwọn ọmọ Réfáì, àti àwọn ará Fílístínì ni a sẹ́gun.

5 Nínú ogun mìíràn pẹ̀lú àwọn ará Fílístínì, Élíhánánì ọmọ Jáírè pa Láhímì arákùnrin Gòláyátì ará àti, Gátì ẹni ti ó ní ọ̀kọ̀ kan tí ó dàbí ọ̀pá ahunsọ.

6 Síbẹ̀síbẹ̀ ninú ogun mìíràn, tí ó wáyé ní Gátì, ọkùnrin títóbi kan wà tí ó ní ìka mẹ́fà ní ọwọ́ Rẹ̀ pẹ̀lú ìka mẹ́fà ní ẹṣẹ̀ Rẹ̀ (24) Mẹ́rìnlélógún lápapọ̀. Òun pẹ̀lú wá láti Ráfà.