11 Àti àwọn ọmọ Gádì ń gbé ọ̀kánkán wọn, ní ilẹ̀ Básánì títí dé Sálíkà:
12 Jóẹ́lì olórí, Ṣáfámù ìran ọmọ, Jánáì, àti Ṣáfátì ni Básánì,
13 Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní:Míkáélì, Mésúlímù Ṣébà, Jóráì, Jákánì, Ṣíà àti Hébérì méje.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ábíháílì, ọmọ Húrì, ọmọ Járóà, ọmọ Gílíádì, ọmọ Míkàẹ́lì, ọmọ Jésíháì, ọmọ Jádò ọmọ Búsì.
15 Áhì, ọmọ Ábídélì, ọmọ Gúnì, olórí ilé àwọn baba wọn.
16 Wọ́n sì ń gbé Gílíádì ní Básánì àti nínú àwọn ìlú Rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbéríko Sárónì, ní agbégbé wọn.
17 Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn-ìdílé, ní ọjọ́ Jótamù ọba Júdà, àti ní ọjọ́ Jéróbóámù ọba Ísírẹ́lì.