22 Éfíráímù baba wọn sọ̀fọ̀ fún wọn ní ọjọ́ púpọ̀, àwọn ìbátan Rẹ̀ wá láti tù ú nínú.
23 Nígbà náà, ó sùn pẹ̀lú, ìyàwó Rẹ̀, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin kan. Ó sì sọ ọ́ ní Béríà nítorí òfò ti wà nínú ìdílé náà.
24 Ọmọbìnrin Rẹ̀ sì jẹ́ Ṣárà, ẹni tí ó kọ́ ìsàlẹ̀ àti òkè Bétí-Hórónì àti Úṣénì sérà pẹ̀lú.
25 Réfà jẹ́ ọmọ Rẹ̀, Rẹ́sẹ́fì ọmọ Rẹ̀,Télà ọmọ Rẹ̀, Táhánì ọmọ Rẹ̀,
26 Ládánì ọmọ Rẹ̀ Ámíhúdì ọmọ Rẹ̀,Élíṣámà ọmọ Rẹ̀,
27 Núnì ọmọ Rẹ̀àti Jóṣúà ọmọ Rẹ̀.
28 Ilẹ̀ wọn àti ìfìdíkalẹ̀ wọn ni Bétélì àti àwọn ìletò tí ó yíká, Náránì lọ sí ìhà ìlà oòrùn, Géṣérì àti àwọn ìletò Rẹ̀ lọ sí ìhà ìwọ̀ oòrùn àti Ṣékémù àti àwọn ìletò Rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Áyáhì àti àwọn ìletò.