42 Jèhósáfátì sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jọba ní ọdún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n ní Jérúsálẹ́mù. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Ásúbà ọmọbìnrin Sílíhì.
43 Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Áṣà baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀.
44 Jèhósáfátì sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ọba Ísírẹ́lì.
45 Níti ìyókù ìṣe Jèhósáfátì àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Júdà?
46 Ó pa ìyókù àwọn tí ń hùwà panṣágà ní ọjọ́ Áṣà bàbá rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà.
47 Nígbà náà kò sí ọba ní Édómù; adelé kan ni ọba.
48 Jèhósáfátì kan ọkọ̀ Táríṣíṣì láti lọ sí Ófírì fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ: nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Ésíónì-Gébérì.