38 Nígbà náà ni ó ṣe agbádá idẹ mẹ́wàá, ọ̀kọ̀ọ̀kan gbà tó ogójì ìwọ̀n Bátì, ó sì wọn ìgbọ̀nwọ́ mẹ́rin, lórí ọ̀kọ̀ọ̀kan ẹsẹ̀ mẹ́wẹ̀ẹ̀wá náà ni agbádá kọ̀ọ̀kan wà.
39 Ó sì fi ẹsẹ̀ márùn ún sí apá ọ̀tún ìhà gúṣù ilé náà àti márùn ún sí apá òsì ìhà àríwá. Ó sì gbé agbádá ńlá ka apá ọ̀tún, ní apá ìlà oòrùn sí ìdojúkọ gúṣù ilé náà.
40 Ó sì tún ṣe ìkòkò, àti ọkọ́ àti àwo kòtò.Bẹ́ẹ̀ ni Hírámù sì parí gbogbo iṣẹ́ tí ó ṣe fún ilé Olúwa fún Sólómónì ọba:
41 Àwọn ọ̀wọ̀n méjì;Ọpọ́n méjì ìparí tí ó wà lókè àwọn ọ̀wọ̀n iṣẹ́;àwọn méjì ní láti bo ọpọ́n méjì ìparí tí ń bẹ lókè àwọn ọ̀wọ̀n;
42 Irínwó (400) pómégíránátè fún iṣẹ́ àwọn méjì, ọ̀wọ́ méjì pómégíránátè fún iṣẹ́ àwọn kan láti bo àwọn ọpọ́n méjì ìparí tí ń bẹ lókè àwọn ọ̀wọ̀n;
43 Ẹṣẹ̀ mẹ́wàá pẹ̀lú agbádá mẹ́wàá wọn;
44 Agbada ńlá náà, àti màlúù méjìlá tí ó wà lábẹ́ rẹ̀;