2 Kíróníkà 14:9-15 BMY

9 Ṣérà ará Kúṣì yàn láti dojú kọ wọ́n, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọmọ ogun pẹ̀lú ọgọ́rùn-ún mẹ́ta kẹ̀kẹ́, wọ́n sì wá láti jìnnà réré bí Máréṣà.

10 Ásà jáde lọ lati lọ bá a. Wọ́n sì mú ibi ogun ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ṣéfátanì lẹ́bá Máréṣà.

11 Nígbà náà, Ásà ké pe Olúwa Ọlọ́run baba a rẹ̀, ó sì wí pé “Olúwa kò sí ẹnìkan bí ì rẹ láti rán aláìlágbára lọ́wọ́láti dójú kọ ẹni ńlá. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run wa, nítorí tí àwa gbẹ́kẹ̀ lé ọ àti ní orúkọ rẹ ni àwa fi wá láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun yìí. Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run wa; má se jẹ́ kí ènìyàn kó ṣẹ́gun rẹ.”

12 Olúwa lu àwọn ará Kúsì bolẹ̀ níwájú Ásà àti Júdà. Àwọn ará Kúsà sá lọ.

13 Ásà àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sá tẹ̀lé wọn ní jìnnà réré sí Gérárì. Ọ̀pọ̀lọpọ̀, àwọn ará Kúṣì ṣubú, wọn kò sì le sán padà mọ́. A fún wọn pa níwájú Olúwa àti ọmọ ogun rẹ̀. Àwọn ọkùnrin Júdà kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógún.

14 Wọ́n pa gbogbo àwọn ìletò tí ó wà ní ẹ̀bá Gérárì, nítorí tí ìpayà Olúwa ti sọ̀kalẹ̀ sórí wọn. Wọ́n kó gbogbo ìkógún àwọn ìletò yìí lọ, níwọ̀n ìgbà tí ọ̀pọ̀ ìkógun ti wà níbẹ̀.

15 Wọ́n kọ lu àwọn ibùdó àwọn darandaran, wọ́n sì gbé àwọn ọ̀wọ́-ẹran àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ àti àwọn ìbákasẹ. Nígbà náà wọ́n padà sí Jérúsálẹ́mù.