1 Ní ọdún kejìlá ọba Áhásì ará Júdà, Hóséà ọmọ Élà jẹ ọba Ísírẹ́lì ní Ṣamáríà, ó sì jẹ fún ọdún mẹsàn án.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i ti ọba Ísírẹ́lì ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀.
3 Ṣálámánesérì ọba Áṣíríà wá sókè láti mú Hóséà, ẹni tí ó ti jẹ fún Ṣálámánésérì ó sì ti san owó òde fún un.
4 Ṣùgbọ́n ọba Ásíríà ríi wí pé Hóséà jẹ́ ọlọ́tẹ̀, nítorí ó ti rán ońsẹ́ sọ́dọ̀ ọba Éjíbítì, kò sì san owó òde mọ́ fún ọba Áṣíríà, gẹ́gẹ́ bí o ti máa ń ṣe ní ọdọdún. Nígbà náà ọba Áṣírìa fi agbára mú-ún, ó sì fi sínú túbú.
5 Ọba Ásíríà gòkè wá sí gbogbo ibi ilé náà, ó sì lọ sí Samáríà, ó sì dúró tìí fún ọdún mẹ́ta.
6 Ní ọdún kẹsàn-án ti Hóṣéà, ọba Áṣíríà mú Ṣamáríà ó sì kó Ísírẹ́lì lọ sí Áṣíríà. Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ ní Hálà, ní Gósánì ní ọ̀dọ̀ Hábónì àti ní ìlú àwọn ará Médáì.
7 Gbogbo eléyìí ṣẹlẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti dẹ́sẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde ní Éjíbítì lábẹ́ agbára Fáráò ọba Éjíbítì. Wọ́n sin ọlọ́run mìíràn