2 Ọba 19:20-26 BMY

20 Nígbà náà Àìṣáyà ọmọ Ámósì rán oníṣẹ́ sí Heṣekíàyà pé: “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ nípa ti Ṣenakérúbù ọba Ásíríà.

21 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀:“ ‘Wúndíá ọmọbìnrin Ṣíónìkẹ́gàn rẹ ó sì fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà.Ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mùmi orí sí ọ gẹ́gẹ́ bí o ti sálọ.

22 Ta ni ìwọ ti bú tí o sì kẹ́gàn rẹ̀?Lórí ta ni ìwọ ti gbé gbé ohùn rẹsókè tí ó sì gbé ojú sókè sí ọ ní ìgbéraga?Lórí ẹni mímọ́ ti Ísírẹ́lì!

23 Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹÌwọ ti ṣe ìkójọpọ̀ èébú sí Olúwa.Ìwọ sì ti sọ pé,“Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ miÈmi sì ti fi dé orí àwọn òkè ńlá,ibi gíga jùlọ ní LébánónìMo sì ti gé igi gíga jùlọ kédárìlulẹ̀, àti àyò igi fírì rẹ̀.Mo ti dé ibi orí òkè ìbùwọ́ ẹ̀gbẹ́ kanibi tí ó dára jù nínú igbó rẹ.

24 Mo ti gbẹ́ kàǹga ní ilẹ̀ àjèjìMo sì mu omi níbẹ̀.Pẹ̀lú àtẹ́lẹṣẹ̀ mi,Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi odò tí ó wà ní Éjíbítì.”

25 “ ‘Ṣé ìwọ kò tí ì gbọ́?Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn mo yàn án.Ní ọjọ́ ogbó ni mo ṣètò rẹ̀;nísinsìn yìí mo ti mú wá sí ìkọjápé ìwọ ti yí ìlú olódi padà díòkítì àlàpà òkúta.

26 Àwọn ènìyàn wọn ń gbẹ nípa,wọ́n ti dàá láàmúwọ́n sì ti sọọ́ di ìtìjú.Wọ́n dà bí koríko ìgbẹ́ lórí pápá,gẹ́gẹ́ bí ọkà tí ó rẹ̀ dànù kí ó tó dàgbà sókè,gẹ́gẹ́ bí fífún ọkà tí ó hù jáde.