31 Láti inú Jérúsálẹ́mù ní àwọn ìyókù yóò ti wáàti láti orí òkè Ṣíónì ni ọ̀pọ̀ àwọn tí ó ṣá àsálà.Ìtara Olúwa àwọn ọmọ ogun yóò ṣe èyí.
32 “Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa ṣọ nípa ti ọba Áṣíríà:“Kò ní wọ ìlú yìítàbí ta ọfà síbí.Kò ní wá níwájú rẹ pẹ̀lúàpáta tàbí kó ìdọ̀tí àgbò sí ọ̀kánkán rẹ.
33 Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá niyóò padà; kì yóò wọ ìlú ńlá yìí,ni Olúwa wí.
34 Èmi yóò dá ààbò bo ìlú ńlá yìí,èmi yóò sì paámọ́ fún èmi tìkálára mi àti fún Dáfídì ìránṣẹ́ mi.”
35 Ní alẹ́ ọjọ́ náà, ańgẹ́lì Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní ibùdó àwọn ará Aṣíríà. Nígbà tí wọ́n sì dìde dúró ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì níbẹ̀ ni gbogbo òkú wà!
36 Bẹ́ẹ̀ ni Ṣenakérúbù ọba Áṣíríà wọ àgọ́ ó sì padà, ó sì padà sí Nínéfè ó sì dúró níbẹ̀.
37 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí ó sùn nínú ilé òrìṣà Nísírókù, ọmọkùnrin rẹ̀ Adiramélékì àti Ṣárésérì gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Árárátì Ésáráhádónì ọmọkùnrin rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.