34 Èmi yóò dá ààbò bo ìlú ńlá yìí,èmi yóò sì paámọ́ fún èmi tìkálára mi àti fún Dáfídì ìránṣẹ́ mi.”
35 Ní alẹ́ ọjọ́ náà, ańgẹ́lì Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní ibùdó àwọn ará Aṣíríà. Nígbà tí wọ́n sì dìde dúró ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì níbẹ̀ ni gbogbo òkú wà!
36 Bẹ́ẹ̀ ni Ṣenakérúbù ọba Áṣíríà wọ àgọ́ ó sì padà, ó sì padà sí Nínéfè ó sì dúró níbẹ̀.
37 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí ó sùn nínú ilé òrìṣà Nísírókù, ọmọkùnrin rẹ̀ Adiramélékì àti Ṣárésérì gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Árárátì Ésáráhádónì ọmọkùnrin rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.