1 Ní ayé ìgbà wọ̀n-ọn-nì Heṣekáyà ṣe àìsàn ó sì wà ní ojú ikú. Wòlíì Àìsáyà ọmọ Ámósì lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: tún ilé rẹ ṣe, ṣùgbọ́n ìwọ yóò kú; o kò níí gbádùn.”
2 Heṣekáyà yí ojú rẹ̀ padà sí ògiri ó sì gbàdúrà sí Olúwa pé,
3 “Rántí, Olúwa mi, bí èmi ṣe rìn níwájú rẹ àti pẹ̀lú bí èmi ṣe jẹ́ olóòtọ́ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn ìfọkànsìn mi tí èmi sì ti ṣe ohun tí ó dára níwájú rẹ.” Heṣekáyà sunkún kíkorò.
4 Kí ó tó di wí pé Àìṣáyà jáde kúrò ní àárin àgbàlá ààfin, ọ̀rọ̀ Olúwa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé.
5 “Lọ padà kí o sì sọ fún Heṣekáyà, olórí àwọn ènìyàn mi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Dáfídì sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti rí omijé rẹ: Èmi yóò wò ó sàn. Ní ọjọ́ kẹta láti ìsinsìnyìí, ìwọ yóò lọ sókè ilé tí a kọ́ fún Olúwa.