2 Ọba 23:28-34 BMY

28 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Jòṣíà, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Júdà?

29 Nígbà tí Jòṣíà jẹ́ ọba, Fáráò Nékò ọba Éjíbítì gòkè lọ sí odò Yúfúrátè láti lọ ran ọba Ásíríà lọ́wọ́. Ọba Jòṣíáyà jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Nékò dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Mégídò.

30 Ìránṣẹ́ Jòṣíáyà gbé ara rẹ̀ wá nínú kẹ̀kẹ́ láti Mègídò sí Jérúsálẹ́mù ó sì sin ín sínú iṣà òkú rẹ̀. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jéhóáhásì ọmọ Jòṣíáyà. Ó fi àmì òróró yàn án, ó sì ṣe é ní ọba ní ipò bàbá a rẹ̀.

31 Jéhóáhásì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́talélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá a rẹ̀ a máa jẹ́ Hámútalì ọmọbìnrin Jeremíáyà; ó wá láti Líbínánì.

32 Ó ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.

33 Fáráò Nékó sì fi sí inú ìdè ní Ríbílà ní ilẹ̀ Hámátì, kí ó má ba à lè jọba ní Jérúsálẹ́mù. Ó sì tan Júdà jẹ fun iye ìwọ̀n ẹgbẹ̀rin talẹ́ntì wúrà kan.

34 Fáráò Nékò ṣe Élíákímù ọmọ Jòṣíàh ní ọba ní ipò baba rẹ̀ Jòsáyà. Ó sì yí orúkọ Élíákímù padà sí Jéhóíákímù. Ṣùgbọ́n ó mú Jéhóáhásì, ó sì gbéé lọ sí Éjíbítì, níbẹ̀ ni ó sì kú.