1 Námánì jẹ́ olórí ogun ọba Árámù. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ Olúwa fún wa ní ìṣẹ́gun fún Árámù. Ó jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
2 Nísinsìnyìí ẹgbẹgbẹ́ láti Árámù ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Ísírẹ́lì, ó sì sin ìyàwó Námánì.
3 Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samáríà! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
4 Námánì lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Ísírẹ́lì ti sọ.