2 Sámúẹ́lì 18:1-7 BMY

1 Dáfídì sì ka àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì mú wọn jẹ balógun ẹgbẹgbẹ̀rún, àti balógun ọrọrún lórí wọn.

2 Dáfídì sì fi ìdámẹ́ta àwọn ènìyàn náà lé Jóábù lọ́wọ́, ó sì rán wọn lọ, àti ìdámẹ́ta lé Ábíṣáì ọmọ Serúíà àbúrò Jóábù lọ́wọ́ àti ìdàmẹ́ta lè Ítaì ará Gítì lọ́wọ́, Ọba sì wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Nítòótọ́ èmi tìkárami yóò sì bá yín lọ pẹ̀lú.”

3 Àwọn ènìyàn náà sì wí pé, “Ìwọ kì yóò bá wa lọ: nítorí pé bí àwa bá sá, wọn kì yóò náání wa, tàbí bí ó tílẹ̀ ṣe pé ìdajì wa kú, wọn kì yóò násní wa, nítorí pé ìwọ nìkan tó ẹgbàarún wa: nítorí náà, ó sì dára kí ìwọ máa ràn wá lọ́wọ́ láti ìlú wá.”

4 Ọba sì wí fún wọn pé, “Èyí tí ó bá tọ́ lójú yin ni èmi ó ṣe.”Ọba sì dúró ní apákan ẹnu odi, gbogbo àwọn ènìyàn náà sì jáde ní ọrọrún àti ní ẹgbẹẹgbẹ̀rún.

5 Ọba sì pàṣẹ fún Jóábù àti Ábíṣáì àti Ítaì pé, “Ẹ tọ́jú ọ̀dọ́mọkùnrin náà Ábúsálómù fún mi.” Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì gbọ́ nígbà tí ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn balógun nítorí Ábúsálómù.

6 Àwọn ènìyàn náà sì jáde láti pàdé Ísírẹ́lì ní pápá; ní igbó Éfúráímù ni wọ́n gbé pàdé ijà náà.

7 Níbẹ̀ ni a gbé pa àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì níwájú àwọn ìránṣẹ́ Dáfídì, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni ó ṣubú lọ́jọ́ náà, àní ẹgbàáwá ènìyàn.