2 Sámúẹ́lì 18:27-33 BMY

27 Álóre náà sì wí pé, “Èmi wo ìsáre ẹni tí ó wà níwájú ó dàbí ìsáré Áhímásì ọmọ Sádókù.”Ọba sì wí pé, “Ènìyàn re ni, ó sì ń mú ìhìn rere wá!”

28 Áhímásì sì dé, ó sì wí fún ọba pé, “Àlàáfíà!” Ó sì wólẹ̀ fún ọba, ó dojúbolẹ̀ ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó fi àwọn ọkùnrin tí ó gbé ọwọ́ wọn sókè sí Olúwa mi ọba lé ọ lọ́wọ́.”

29 Ọba sì béèrè pé, “Àlàáfíà ha wà fún Ábúsálómù, ọmọdékùnrin náà bí?”Áhímásì sì dáhùn pé, “Nígbà tí Jóábù rán ìránṣẹ́ ọba, àti èmi ìránṣẹ́ rẹ̀, mo rí ọ̀pọ̀ ènìyàn, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ìdí rẹ̀.”

30 Ọba sì wí fún un pé, “Yípadà kí o sì dúró nìhìn-ín.” Òun sì yípadà, ó sì dúró jẹ́ẹ́.

31 Sì wò ó, Kúṣì sì wí pé, “Ìhìnrere fún Olúwa mi ọba: nítorí tí Olúwa ti gbẹ̀san rẹ lónìí lára gbogbo àwọn tí ó dìde sí ọ.”

32 Ọba sì bi Kúṣì pé, “Àlàáfíà kọ́ Ábúsálómù ọ̀dọ́mọdékùnrin náà wá bí?”Kúṣì sì dáhùn pe, “Kí àwọn ọ̀ta Olúwa mi ọba, àti gbogbo àwọn tí ó dìde sí ọ ní ibi, rí bí ọ̀dọ́mọdékùnrin náà.”

33 Ọba sì kẹ́dùn púpọ̀ ó sì gòkè lọ, sí yàrá tí ó wà lórí òkè ibodè, ó sì sunkún; bayìí ni ó sì ń wí bí ó ti ń lọ, “Ọmọ mi Ábúsálómù! Ọmọ mi! Ọmọ mí Ábúsálómù! Áì! Ìbáṣepé èmi ni ó kú ní ipò rẹ̀! Ábúsálómù ọmọ mi, ọmọ mi!”